Kíni à bá fi dúpẹ́ lọ́wọ́ Olódùmarè fún àṣeyọrí jíjáde tí a ti jáde kúrò nínú aríremáse nàìjíríà, nípasẹ̀ iṣẹ́ tó gbé lé Màmá wa lọ́wọ́: Ìyá-Ààfin Modúpẹ́ Onítirí-Abíọ́lá

Ìdí ọpẹ́ wa ni pé, ṣé bí àwa náà ìbá ti máa yí láti inú gbèsè kan sí òmíràn nìyí?

Ìròyìn tí ó tẹ̀ wá lọ́wọ́ lórí ayélujára sọ pé bílíọ̀nù kan-àbọ̀, ó lé ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọrin dọ́là ni gbèsè tí ìlú agbésùnmọ̀mí nàìjíríà tó ń fi agídí dúró sórí ilẹ̀ wa D.R.Y, tún ti yá lọ́wọ́ ìlé-ìfowó-pamọ́ àgbáyé,gbèsè ń yí lu gbèsè fún wọn níbẹ̀.

Ṣé èyí kò tilẹ̀ kàn wá tí kò bá ṣe ti ipá tí wọ́n fi dúró lórí ilẹ̀ wa, Democratic Republic of the Yoruba (D.R.Y). A ti ṣe ìkéde òmìnira wa, ní ogúnjọ́ oṣù Bélú, ẹgbàá ọdún ó lé méjìlélógún, bẹ́ẹ̀ ni a ti bẹ̀rẹ̀ ìṣèjọba-ara-ẹni ní ọjọ́ kéjìlá oṣù Igbe ẹgbàá ọdún ó lé mẹ́rìnlélógún, nítorí èyí, gbèsè yòówù tí ajẹgàba Nàìjíríà ìbáà jẹ, kò kàn wá.

Gẹ́gẹ́bí ìròyìn náà ṣe sọ, ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta mílíọ̀nù dọ́là yóò wà fún “ọ̀rọ̀-ìṣèjọba tí ó fa ìlọsẹ́yìn fún ètò ẹ̀kọ́ àti ti ìlera.” Àwa ò mọ ìtúmọ̀ gbólóhùn gbọọrọgbọ yí, ìgbà tí wọ́n bá ti fẹ́ kó’wó jẹ ni wọ́n máa ń sọ àwọn òyìnbó òfò tí kò ní ìtumọ̀.

Ṣùgbọ́n ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ó lé ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́rin dọ́là míràn wà fún ètò ìwòsàn fún àwọn obìnrin, ọmọdé àti ọmọ tí kò kọjá ọdún mẹ́tàlá, tí a bá lọ tí a bá bọ̀, ibi kan máa wà tí ọ̀rọ̀ abẹ́rẹ́-àjẹsára máa jẹyọ.

Fún ìdí èyí, kí àwa I.Y.P ó ṣọ́ra dáadáa, nítorí àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé náà ni wọ́n kọ́kọ́ máa ń dojú-kọ. Ohun tí ó bá ti yàtọ̀ sí ohun tí Ìjọba-Adelé wa bá sọ, kí a máṣe lọ́wọ́ síi.

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.